Monday 28 October 2019

Owo te tewon de, to ji okada ni Bariga


Owo tewon de, to ji okada ni Bariga
Ade Oniroyin
Owo ileese olopaa ti te okunrin kan to sese de lati ogba ewon, Folarin Moses lori esun po fipa gba okada lowo okunrin kan, Olayemi Agbamuche laduugbo Bariga niluu Eko.
Nigba to n fidii isele ohun mule, alukoro ileese olopaa ipinle Eko, Bala Elkana salaye pe bi olobo isele ohun se taoga olopaa tesan Bariga lo ti dawon olopaa sita, ti won si mu odaran naa, pelu afikun pe laipe yii ni won da odaran naa sile logba ewon lori esun kan naa.

Owo te Deborah to ji moto jiipu gbe


Owo te Deborah to ju moto jiipu gbe
Ade Oniroyin
Owo ileese olopaa ipinle eko ti te omobinrin alagbata kan, Deborah Nwachukwu lori esun po ji moto jiipu kan, foonu was arrested for allegedly stealing a Jeep, Samsung S10, aago owo, awon ohun ikunra oloorun towo re to milionu kan naira ati owo gbe lodo okunrin kan ti won poruko re ni Patrick laduugbo Ikeja nipinle Eko.
Alukoro ileese olopaa, Bala Elkana salaye pe Patrick pade Nwachukwu  nile-itaja kan, o si pee lati wa baa tun ile re se pelu adehun lati fun un ni egberun lona ogun naira. Gege bo se wi, Patrick ni adehun a ti jo lajosepo naa wa laarin won. O soo di mimo pe, leyin ti won lasepo tan, ni Patrick sun lo.
“ Bo se sakiyesi pe, okunrin yi ti sun lo fonfon. Nise lo ko foonu re mejeeji, aago owo ohun ikunra oloorun, owo ati moto jiipu re. Bayii lo si salo, leyin to ti tii mole. Awon osise olopaa otelemuye ti oga olopaa tesan Ikeja, Gbenga Ogunsakin lewaju re lo si mu omobinrin ohun, ti won si gba gbogbo ohun to ji na. Won ti gbe odaran yi lo siwaju ile-ejo, ti won si ti fi pamo si ahamo.

Kayeefi! Baba pa omo re lasiko to n ba iyawo re ja


Kayeefi!
Baba pa omo re lasiko to n ba iyawo re ja
Ade Oniroyin
Owo ileese olopaa ipinle Eko ti te okunrin kan,  Ayobami Isiaka lori esun po pa omo re, omo odun kan laduugbo Ijaye nitosi Iseri niluu Eko.
Gege bi alukoro ileese olopaa ipinle Eko, Bala Elkana se so ninu atejade kan to fi sita lojo sannde ana, Ayobami pa omo re ohun t’oruko re n je Nana lasiko tie de aiyede kan waye laarin oun atiyawo re. akoroyin wa gbo pe, nise ni okunrin yii sadeede gba omo lowo iyawo re, to si la ori re mole.
O soo di mimo pe, nise loei Nana fo yanga yanga loju ese nibe pelu afikun pe omooya Ayobami lo mu esun ohun lo si ago olopaa. Ninu oro re, Elkana ni “lojo sannde, ojo kerindinlogbon osu yii ni deedee aago meje ku iseju mewaa, okunrin kan,  Alaaji Garuba Isiaka mu esun lo si ago olopaa pe lojo naa, lasiko toun wa ni Berger, ni aburo oun kan, Alaaji Mohammad Isiaka foonu pe, Ayobami Isiaka ti fi tipatipa gba omo re obinrin omo odun kan, Nana lowo iya re, to si lee mole”
“Ori omo naa fo tutu, to si ku loju ese nibe. Ti ko ba si si tawon olopaa to tete de ibi isele ohun, nise lawon eeyan to wa nitosi ki ba luu pa. Laipe ni yoo si foju ba ile-ejo.”

Friday 26 July 2019

SEYI MAKINDE foruko awon komisanna ranse sile asofin -bee lo tun yan igbimo ti yoo gb’oro awon T’AJIMOBI da duro lenu ise wo

Yanju Adegboyega
SEYI MAKINDE foruko awon komisanna ranse sile asofin
-bee lo tun yan igbimo ti yoo gb’oro awon T’AJIMOBI da duro lenu ise wo
Lati le je ki ise ilu to gbe lowo rorun fun un, Gomina ipinle Oyo, Onimo-ero Seyi Makinde ti fi oruko awon eeyan merinla ranse sile igbimo asofin ipinle naa lati sayewo finni-finni fun won. Lara awon to foruko won ranse la ti ri Amofin Adeniyi Farinto; Ogbeni Adeniyi Olabode Adebisi; Onarebu Muyiwa Jacob Ojekunle; Ojogbon Oyewo Oyelowo; Amofin Seun Asamu; Amofin Lasunkanmi Ojeleye; Ogbeni Rahmon Abiodun Abdulraheem ati Oloye Bayo Lawal.
Awon to ku ni Onarebu Funmilayo Orisadeyi to je obinrin kan soso laarin won, Dokita Bashir Abiodun Bello; Onarebu Wasiu Olatunbosun; Ojogbon Daud Sangodoyin; Ogbeni Akinola Ojo ati Onarebu Kehinde Ayoola to ti figba kan je abenugan kile igbimo asofin ipinle Oyo lasiko isejoba Alaaji Lam Adesina.
Ewe, Gomina Seyi Makinde ti sagbekale igbimo eleni mejila kan ti yoo sagbeyewo ilana ti gomina tele, Sineto Abiola Ajimobi gba lati dawon eeyan kan duro lenu ise ijoba laarin odun 2011 si 2019. Gege baa se gbo, opo awon eeyan lo ti n ko’we ehonu ranse sijoba lat’igba ti Makinde ti depo ase pe, nise nijoba Ajimobi kan mo on mo fi iwa etaanu da won duro lenu ise ni.
Ni bayii, ijoba ti wa ke sawon eeyan ti oro ohun kan lati ko iwe ranse si yara ketadinlogbon nileese to n ri soro awon osise ijoba to wa ni sekiteriati ko to di ojo monde ojo karun-un osu kejo.

Friday 19 July 2019

Egbe omo bibi ile Ibadan gba MAKINDE nimoran lori siso egbin d’oro


Egbe omo bibi ile Ibadan gba MAKINDE nimoran lori siso egbin d’oro
Yanju Adegboyega
Bi ijoba ipinle Oyo labe akoso Onimo-ero Seyi Makinde se se agbekale ile-ejo alagbeeka lori imototo ayika, egbe omo bibi ile Ibadan, Central Council of Ibadan Indigenes, CCII ti gba ijoba nimoran lati sise lori siso egbin di oro, eyi to je okan lara ileri to se lasiko ipolongo ibo to koja.
Aare egbe CCII, Oloye Yemi Soladoye lo pe ipe ohun nibi ipade kan to waye lori ona ti ko ba ofin mu tawon eeyan fi n pa egbin mo nipinle Oyo. O woye pe, tijoba ba seto siso egbin d’oro. Nise lo ye ki won maa sanwo fawon to n da egbin nu, eyi ti won fi tun n gb’owo lowo won. Soladoye wa ro ijoba ipinle Oyo lati tete bere ise lori ibudo ti won ti n so egbin d’owo to wa laduugbo Orita Aperin niluu Ibadan, nitori ti won ti paa ti fun igba pipe.
Olori osise oba nipinle Oyo, Alaaja Ololade Hamdalat Agboola to se kokaari ipade ohun war o gbogbo awon to wa nibe lati tan ihinrere pi pa egbin mo lona ti ko fin ii fa wahala siluu.

Thursday 27 June 2019

The INTERNET LORD is based in Ibadan Oyo State Nigeria

The INTERNET LORD is based in Ibadan Oyo State Nigeria. He is no one but Smith Chukwuemeka Eze